Uncategorized

Ṣé Ambode ti darapọ̀ mọ ẹgbẹ ́òṣèlú Labour Party?

Àwọn àtẹ̀jáde tó ń tàn ràn-ín l’orí ayélujára gbé àhesọ kan pé Akinwunmi Ambode, gómìnà ìpínlè Èkó tẹĺẹ̀rí ti darapọ̀ mọ́ ẹgbẹ ́òṣèlú àwọn òṣìṣẹ́.

Àtẹ̀jáde náà sọ pé gómìnà ìpínlè Èkó tẹ́lẹ̀ rí náà fẹ́ díje fún ipò gómìnà ni ọdún 2023 labẹ àsìá ẹgbẹ́ òṣèlú àwọn òṣìṣẹ.

Ní ọjọ́ karún, oṣù keje,Leadership Scorecard, ilé ìwé ìròyìn kan gbe àhesọ yìí, pẹ̀lú àtẹ̀jáde tí a lérò pé ó wá láti ọdọ Ambode, èyí tí o gba àwọn ọ̀dọ́ ni ìmòrán pé kí wọ́n gba káàdì ìdìbò àlálòpẹ́, ṣáájú ìdìbò tó ń bọ̀.

“Àwọn ọ̀dọ́ ń bọ̀. Agbára wà lọ́wọ́ wọn. Ẹ lọ gba káàdì ìdìbò àlálòpẹ́ yín. Ọjọ́ iwájú yín ti sún mọ́lé.”

Ní ọjọ́ keje, awuyewuye lórí àhesọ pé Ambode fi ẹgbẹ́ òṣèlú All Progressives Party (APC), èyí ní ẹgbẹ́ tí ń ṣe ìjọba àpapọ̀ lọ́wọ́ sílẹ tàn rán-ín lóri Twitter, ìkànnì abẹ́yẹfò.

Ifiidiododomulẹ

Comment here

I accept the Terms and Conditions and the Privacy Policy